Ọwọ́ tí ọ̀gẹ̀dẹ̀ bá gbé, ara rẹ̀ ló fi ń nà o.

Àwọn ẹgbẹ́ kan ní Ìlú Èkó, tí wọ́n pe ara wọn ní “De Renaissance Patriots Foundation,” ti kọ ìwé sí Wèrè-Ìlú-Èkó, Babajídé Sanwó-Olú, gómìnà Nàìjíríà tó fipá jẹgàba ní Ìpínlẹ̀-Èkó ti Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá, pé kí ó wá ṣe àlàyé lórí ọ̀rọ̀ ọgọ́run mílíọ̀nù owó dọ́là ilẹ̀ Amẹ́ríkà tí ọmọ Fúlàní, Aliko Dangote, sọ pé òun san fún ilẹ̀ tí òun kọ́ ilé-iṣẹ́ Ìfọ’po Rọ̀bì sí ní agbègbè Ìbèjù-Lekki.

❗PÀJÁWÌRÌ FÚN ÀÀBÒ❗KÁÀKIRI GBOGBO ÌPÍNLẸ̀ YORÙBÁ TÍTÍ DÉ OLD Ọ̀YỌ́ EMPIRE, Ẹ MÁA YA FỌ́TÒ FÚLÀNÍ, OLỌ́PA, OLÓṢÈLÚ, SÓJÀ, TÍ Ẹ BÁ FURA SÍ ÌRÌN ÀTI ÌṢESÍ WỌN NÍ AGBÈGBÈ YÍN. KÍ Ẹ FI ṢỌWỌ́ SÍ BÀBÁ ÌJÌNLẸ̀ +905367341665 (WHATSAPP). (ÌKÉDE… Pín Sórí Àgbàgbé X (Twitter)

Gẹ́gẹ́bí ẹgbẹ́ náà ṣe sọ, ó lé ní ẹgbẹ̀rún méje ékà ilẹ̀ tí wọ́n gbà lọ́wọ́ àwọn onílẹ̀ ní agbègbè náà láì san owó “gbà, má bínú” fún àwọn ènìyàn náà. Wọ́n ní ohun tí àwọn ènìyàn agbègbè náà gbọ́ tẹ́lẹ̀ ni pé ọ̀fẹ́ ni wọ́n fún Dangote ní ilẹ̀ náà látàrí kí ilé-iṣẹ́ Ìfọpo ọ̀ún ṣáà lè wá sí agbègbè Ibèjù-Lekki.

Wọ́n wá nbérè lọ́wọ́ Sanwó-Olú pé, ọgọ́run mílíọ̀nù dọ́là tí Dangote ní òun san fún ilẹ̀ ọ̀ún, tani, gan-gan, ni ẹni tí ó gba owó yí, àti pé àpò-ìfowópamọ́ wo, gan-gan, ní ilé-iṣẹ́ Ìfowópamọ́ wo, ni owó náà wọ’lé sí. Wọ́n tún nbérè pé kíni, gan, tí wọ́n lo owó ọ̀ún fún.

Ó ṣe ni láanú pé, àti ẹgbẹ́ tó kọ’wé sí Sanwó-Olú, àti Sanwó-Olú fún’ra rẹ̀, ọ̀daràn ni àwọn méjèèjì!

Ṣé ẹgbẹ́ De Renaissance Patriots Foundation yí kò gbọ́ pé Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá, èyí tí Ìpínlẹ̀ Èkó wà lára rẹ̀, ti di Orílẹ̀-Èdè Aṣèjọba-Ara-Ẹni láti ọjọ́ kéjìlá oṣù igbe, ẹgbàá ọdún ó lé mẹ́rin-lé-l’ogún ni? àti pé láti ọjọ́ náà, kò sí ohunkóhun t’ó njẹ́ ẹgbẹ́ ní Orílẹ̀-Èdè Yorùbá, láì sí àṣẹ ìjọba Democratic Republic of the Yoruba?

The democratic republic of the yoruba is a new sovereign nation from april 12th 2024

Bẹ́ẹ̀ náà ni Sanwó-Olú kìí ṣe gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó ní Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá. Nítorí èyí, èwo làbùrọ̀ máa kọ ìwé sí Sanwó-Olú lórí ọ̀rọ̀ tí ó jẹ mọ́ ilẹ̀ Orílẹ̀-Èdè Yorùbá, nígbàtí Orílẹ̀-Èdè Yorùbá ti ní Ìjọba tirẹ̀.

Ẹ̀yin ọmọ Ìbílẹ̀ Yorùbá, ìdí nìyí tí a nílati ṣọ́ra gidi ní àkókò yí, ká má ṣe ṣẹ̀ sí òfin Orílẹ̀-Èdè Yorùbá.

Nípa kí kọ ìwé sí Sanwó-Olú, tí Sanwó-Olú náà kì dẹ̀ nṣe ara Ìjọba Orílẹ̀-Èdè Yorùbá, ṣùgbọ́n tí ó jẹ́ ìkan lára àwọn ajẹgàba Nàìjíríà tí wọ́n njẹgàba lórí ilẹ̀ Yorùbá, àwọn tí wọ́n pe’ra wọn ní De Renaissance Patriots Foundation yí, ti fi ara wọn hàn gẹ́gẹ́bí ara àwọn tí ó fọwọ́ sí jíjẹgàba tí Sanwó-Olú àti ijọba Nàìjíríà jẹ gàba sí orí ilẹ̀ Yorùbá, D.R.Y; èyí sì jẹ́ ọ̀ràn dídá gbáà l’ọrùn àwọn ọmọ-ẹgbẹ́ De Renaissance Patriots Foundation náà, lábẹ́ òfin Orílẹ̀-Èdè Yorùbá. Ìyẹn èkíní.

Èkejì, Sanwó-Olú tí wọ́n kọ ìwé sí, a kò gbọ́ pé Sanwó-Olú sọ fún àwọn ẹgbẹ́ yí pé èrèdí kíni wọ́n ṣe kọ ìwé sí òun nígbàtí òun kìí ṣe ara Ìjọba Orílẹ̀-Èdè Yorùbá!

Èyí túmọ̀ sí pé Sanwó-Olú ṣì nrí ara rẹ̀ gẹ́gẹ́bí gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó, l’ẹhìn tí ìpínlẹ̀ Èkó, àti ilẹ̀ Yorùbá tó kù, ti kúrò ní Nàìjíríà ní ogúnjọ́ oṣù bélú, ẹgbàá ọdún ó lé méjì-lé-l’ogún, tí a dẹ̀ ti gbé ìjọba Orílẹ̀-Èdè Yorùbá sórí àlééfà láti ọjọ́ kéjìlá oṣù igbe, ẹ̀gbàá ọdún ó lé mẹ́rìn-lé-l’ogún!

Ẹrí nlá gbáà ni eléyi jẹ́, láti fi ẹjọ́ Sanwó-Olú sùn ilé-ẹjọ́ àgbáyé pé ó nṣe bíi gómìnà ìpínlẹ̀ Èkó l’ẹhìn tí ìpínlẹ̀ Èkó kò sí lábẹ́ Nàìjíríà mọ́, ṣùgbọ́n tí ó jẹ́ ara Orílẹ̀-Èdè Aṣèjọba-Ara-Ẹni ti D.R.Y !

Bẹ́ẹ̀ náà ni èyí jẹ́ ẹ̀rí pé Nàìjíríà, èyí tí Sanwó-Olú nṣiṣẹ́ fún, ṣì nka ilẹ̀ Yorùbá mọ́ ìlú Nàìjíríà l’ẹhìn tí Yorùbá àti ilẹ̀ abínibí wa ti jáde kúrò nínú Nàìjíríà, tí a sì ti ní ìjọba ti’wa.

Ká Ìròyìn Síwájú sí:

Nípa ti Dangote fún’ra rẹ̀, àti ẹnikẹ́ni tí ìbáàwù tí ó ní òun san ọgọ́run bílíọ̀nù dọ́là fún lórí ọ̀rọ̀ ilẹ̀ tí ó wà ní Ìbẹ̀jú-Lekki ọ̀ún, ẹ fi ìyẹn sílẹ̀ fún Ìjọba-Adelé Orílẹ̀-Èdè Olómìnira Tiwantiwa ti Yorùbá, láti dá sẹ̀ríà fún wọn ní kété tí Ìjọba-Adelé bá ti wọ inú oríkò Ilé-Iṣẹ́ Ìjọba wa gbogbo ní Ilẹ̀ Yorùba.

Tiwa, gẹ́gẹ́bí ọmọ ìbílẹ̀ Yorùbá, ní àkókò yí, ni kí á máa fi gbogbo àwọn ẹ̀rí tí a ní lọ́wọ́ nípa aṣemáṣe wọ̀nyí, ṣọwọ́ sí àwọn aṣíwájú wa ní D.R.Y – àwọn nkan bíi fọ́tò tàbí fídíò àwọn ọlọ́pa tàbí òṣìṣẹ́ lábẹ́ Nàìjíríà tí wọ́n ṣì nlúgọ sorí ilẹ̀ náà ní Ìbẹ̀jù-Lekki, tàbí òṣìṣẹ́ Dangote tí ó bá nfi ìyà jẹ ọmọ Yorùbá níbẹ̀, tàbí tí ó nṣe aṣemáṣe kankan níbẹ̀.

Àti Sanwó-Olú, àti Nàìjíríà, àti Dangote, ọjọ́ ìdájọ́ wọn ti dé.